a Isa 15–16; 25.10-12; Jr 48; El 25.8-11; Sf 2.8-11.

Amos 2:1-3

1 aÈyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu,
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí ó ti sun ún, di eérú,
egungun ọba Edomu
2Èmi yóò rán iná sí orí Moabu
èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run.
Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo
pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè
3Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò
Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,”
ni Olúwa wí.
Copyright information for YorBMYO